17
Ìdáhùn Jobu
“Ẹ̀mí mi bàjẹ́,
ọjọ́ mi ni a ti gé kúrú,
isà òkú dúró dè mí.
Nítòótọ́ àwọn ẹlẹ́yà wà lọ́dọ̀ mi,
ojú mi sì tẹ̀mọ́ ìmúnibínú wọn.
 
“Fi fún mi Olúwa, ìlérí tí ìwọ fẹ́;
ta ni yóò le ṣe ààbò fún mi?
Nítorí pé ìwọ ti sé wọ́n láyà kúrò nínú òye;
nítorí náà ìwọ kì yóò gbé wọn lékè.
Ẹni tí ó sọ ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn dídún fún àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ fún èrè,
òun ni ojú àwọn ọmọ rẹ̀ yóò mú òfo.
 
“Ọlọ́run ti sọ mi di ẹni òwe fún àwọn ènìyàn;
níwájú wọn ni mo dàbí ẹni ìtutọ́ sí ní ojú.
Ojú mí ṣú bàìbàì nítorí ìbìnújẹ́,
gbogbo ẹ̀yà ara mi sì dàbí òjìji.
Àwọn olódodo yóò yanu sí èyí,
ẹni aláìṣẹ̀ sì bínú sí àwọn àgàbàgebè.
Olódodo pẹ̀lú yóò di ọ̀nà rẹ̀ mú,
àti ọlọ́wọ́ mímọ́ yóò máa lera síwájú.
 
10 “Ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti gbogbo yín,
ẹ yípadà, kí ẹ si tún padà nísinsin yìí;
èmi kò le rí ọlọ́gbọ́n kan nínú yín.
11 Ọjọ́ tí èmi ti kọjá, ìrò mi ti fà yá,
àní ìrò ọkàn mi.
12 Àwọn ènìyàn wọ̀nyí ń ṣọ́ òru di ọ̀sán;
wọ́n ní, ìmọ́lẹ̀ súnmọ́ ibi tí òkùnkùn dé.
13 Bí mo tilẹ̀ ní ìrètí, ipò òku ní ilé mi;
mo ti tẹ́ ibùsùn mi sínú òkùnkùn.
14 Èmi ti wí fún ìdíbàjẹ́ pé, ìwọ ni baba mi,
àti fún kòkòrò pé, ìwọ ni ìyá mi àti arábìnrin mi,
15 ìrètí mi ha dà nísinsin yìí?
Bí ó ṣe ti ìrètí mi ni, ta ni yóò rí i?
16 Yóò sọ̀kalẹ̀ lọ sínú ipò òkú,
nígbà tí a jùmọ̀ sinmi pọ̀ nínú erùpẹ̀ ilẹ̀?”