35
Olóòtítọ́ ni Ọlọ́run
Elihu sì wí pe:
“Ìwọ rò pé èyí ha tọ́, tí ìwọ wí pé,
òdodo mi ni èyí níwájú Ọlọ́run?
Nítorí tí ìwọ wí pé èrè kí ní yóò jásí fún ọ,
tàbí èrè kí ni èmi yóò fi jẹ́ ju èrè ẹ̀ṣẹ̀ mi lọ.
 
“Èmi ó dá ọ lóhùn
àti àwọn ẹgbẹ́ rẹ pẹ̀lú rẹ.
Síjú wo ọ̀run; kí o rí i, kí ó sì
bojú wo àwọsánmọ̀ tí ó ga jù ọ́ lọ.
Bí ìwọ bá dẹ́ṣẹ̀, kí ni ìwọ fi sẹ̀ sí?
Tàbí bí ìrékọjá rẹ di púpọ̀, kí ni ìwọ fi èyí nì ṣe sí i?
Bí ìwọ bá sì ṣe olódodo, kí ni ìwọ fi fún un,
tàbí kí ni òun rí gbà láti ọwọ́ rẹ wá?
Ìwà búburú rẹ ni fún ènìyàn bí ìwọ;
òdodo rẹ sì ni fún ọmọ ènìyàn.
 
“Nípa ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìninilára, wọ́n mú ni kígbe;
wọ́n kígbe nípa apá àwọn alágbára.
10 Ṣùgbọ́n kò sí ẹni tí ó wí pé,
‘Níbo ni Ọlọ́run Ẹlẹ́dàá mi wà tí ó sì fi orin fún mi ní òru;
11 tí òun kọ́ wa ní ẹ̀kọ́ jù àwọn ẹranko ayé lọ,
tí ó sì mú wa gbọ́n ju àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run lọ?’
12 Nígbà náà ni wọ́n ń ké ṣùgbọ́n Ọlọ́run kò dáhùn
nítorí ìgbéraga ènìyàn búburú.
13 Nítòótọ́ Ọlọ́run kì yóò gbọ́ ọ̀rọ̀ asán;
bẹ́ẹ̀ ní Olódùmarè kì yóò kà á sí.
14 Bí ó tilẹ̀ ṣe pé ìwọ wí pé ìwọ kì í rí i,
ọ̀rọ̀ ìdájọ́ ń bẹ níwájú rẹ,
ẹni tí ìwọ sì gbọdọ̀ dúró dè.
15 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí nítorí tí ìbínú rẹ̀ kò tí fìyà jẹ ni,
òun kò ni ka ìwà búburú si?
16 Nítorí náà ní Jobu ṣe ya ẹnu rẹ̀
lásán ó sọ ọ̀rọ̀ di púpọ̀ láìsí ìmọ̀.”