39
Agbára Ọlọ́run
“Ìwọ mọ àkókò ìgbà tí àwọn ewúrẹ́ orí àpáta ń bímọ?
Ìwọ sì lè kíyèsi ìgbà tí abo àgbọ̀nrín ń bímọ?
Ìwọ lè ka iye òṣùpá tí wọn ń pé,
ìwọ sì mọ àkókò ìgbà tí wọn ń bímọ.
Wọ́n tẹ ara wọn ba, wọ́n bímọ,
wọ́n sì mú ìkáàánú wọn jáde.
Àwọn ọmọ wọn rí dáradára, wọ́n dàgbà nínú ọ̀dàn;
wọ́n jáde lọ, wọn kò sì tún padà wá sọ́dọ̀ wọn.
 
“Ta ni ó jọ̀wọ́ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ oko lọ́wọ́?
Tàbí ta ní ó tú ìdè kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó,
èyí tí mo fi aginjù ṣe ilé fún,
àti ilẹ̀ iyọ̀ ní ibùgbé rẹ̀.
Ó rẹ́rìn-ín sí ariwo ìlú,
bẹ́ẹ̀ ni òun kò sì gbọ́ igbe darandaran.
Orí àtòlé òkè ńlá ni ibùjẹ oko rẹ̀,
òun a sì máa wá ewé tútù gbogbo rí.
 
“Àgbáǹréré ha jẹ́ sìn ọ́ bí?
Tàbí ó jẹ́ dúró ní ibùjẹ ẹran rẹ ní òru?
10 Ìwọ le fi òkun tata de àgbáǹréré nínú aporo?
Tàbí ó jẹ́ máa fa ìtulẹ̀ nínú aporo oko tọ̀ ọ́ lẹ́yìn?
11 Ìwọ ó gbẹ́kẹ̀lé e nítorí agbára rẹ̀ pọ̀?
Ìwọ ó sì fi iṣẹ́ rẹ lé e lọ́wọ́?
12 Ìwọ le gbẹ́kẹ̀lé pé, yóò mú èso oko rẹ̀ wá sílé,
àti pé yóò sì kó ọ jọ sínú àká rẹ?
 
13 “Ìwọ ni yóò ha fi ìyẹ́ dáradára fún ọ̀kín bí,
tàbí ìyẹ́ àti ìhùhù bo ògòǹgò?
14 Ó yé ẹ̀yìn rẹ̀ sílẹ̀ lórí ilẹ̀,
a sì mú wọn gbóná nínú ekuru;
15 tí ó sì gbàgbé pé, ẹsẹ̀ lè tẹ̀ wọ́n fọ́,
tàbí pé ẹranko igbó lè tẹ̀ wọ́n fọ́.
16 Kò ní àánú sí àwọn ọmọ rẹ̀ bí ẹni pé wọn kì í ṣe tirẹ̀;
asán ni iṣẹ́ rẹ̀ láìní ìbẹ̀rù;
17 nítorí pé Ọlọ́run kò fún un ní ọgbọ́n,
bẹ́ẹ̀ ni kò sì fi ìpín òye fún un.
18 Nígbà tí ó gbé ara sókè,
ó gan ẹṣin àti ẹlẹ́ṣin.
 
19 “Ìwọ ni ó fi agbára fún ẹṣin bí,
tàbí ṣé ìwọ ni ó fi gọ̀gọ̀ wọ ọrùn rẹ̀ ní aṣọ?
20 Ìwọ le mú fò sókè bí ẹlẹ́ǹgà?
Ògo èémí imú rẹ ní ẹ̀rù ńlá.
21 Ó fi ẹsẹ̀ halẹ̀ nínú àfonífojì, ó sì yọ̀ nínú agbára rẹ̀;
ó lọ jáde láti pàdé àwọn ìhámọ́ra ogun.
22 Ó fi ojú kékeré wo ẹ̀rù, àyà kò sì fò ó;
bẹ́ẹ̀ ni kì í sì í padà sẹ́yìn kúrò lọ́wọ́ idà.
23 Lọ́dọ̀ rẹ ni apó-ọfà ń mì pẹkẹpẹkẹ,
àti ọ̀kọ̀ dídán àti àpáta.
24 Ó fi kíkorò ojú àti ìbínú ńlá gbé ilé mi,
bẹ́ẹ̀ ni òun kò sì gbà á gbọ́ pé, ìró ìpè ni.
25 Ó wí nígbà ìpè pé, Háà! Háà!
Ó sì gbóhùn ogun lókèèrè réré,
igbe àwọn balógun àti ìhó ayọ̀ ogun wọn.
 
26 “Àwòdì ha máa ti ipa ọgbọ́n rẹ̀ fò sókè,
tí ó sì na ìyẹ́ apá rẹ̀ sí ìhà gúúsù?
27 Idì ha máa fi àṣẹ rẹ̀ fò sókè,
kí ó sì lọ tẹ́ ìtẹ́ rẹ̀ sí òkè gíga?
28 Ó ń gbé, ó sì ń wò ní orí àpáta,
lórí pàlàpálá òkúta àti ibi orí òkè.
29 Láti ibẹ̀ lọ ni ó ti ń wá oúnjẹ kiri,
ojú rẹ̀ sì ríran rí òkè réré.
30 Àwọn ọmọ rẹ̀ pẹ̀lú a máa mu ẹ̀jẹ̀,
níbi tí òkú bá gbé wà, níbẹ̀ ni òun wà pẹ̀lú.”