Saamu 99
1 Olúwa jẹ ọba;  
jẹ́ kí ayé kí ó wárìrì  
Ó jókòó lórí ìtẹ́ kérúbù  
jẹ́ kí ayé kí ó wárìrì.   
2 Olúwa tóbi ní Sioni;  
Ó sì ga jù gbogbo orílẹ̀-èdè lọ.   
3 Kí wọ́n sì yin orúkọ rẹ̀ tí ó tóbi  
tí ó ni ẹ̀rù, Mímọ́ ni Òun.   
   
 
4 Ọba náà ní agbára, ó sì fẹ́ òdodo,  
ìwọ fi ìdí àìṣègbè múlẹ̀;  
ìwọ ṣe ohun tí ó tọ́ àti ohun tí ó yẹ nínú Jakọbu.   
5 Gbígbéga ni Olúwa Ọlọ́run wa  
ẹ foríbalẹ̀ níbi ẹsẹ̀ rẹ̀; ó jẹ́ mímọ́.   
   
 
6 Mose àti Aaroni wà nínú àwọn àlùfáà rẹ̀  
Samuẹli wà nínú àwọn tí ó ń ké pe orúkọ rẹ̀  
wọ́n ké pe Olúwa, ó sì dá wọn lóhùn.   
7 Ó sọ̀rọ̀ sí wọn nínú ọ̀wọ́n àwọsánmọ̀,  
wọ́n pa ẹ̀rí rẹ̀ mọ́ àti ìlànà tí ó fún wọn.   
   
 
8 Olúwa Ọlọ́run wa, ó dá wọn lóhùn;  
ó jẹ́ Ọlọ́run tí ó ń dáríjì àwọn ọmọ Israẹli  
ìwọ tí ó ń fi ìyà àìṣedéédéé wọn jẹ wọ́n.   
9 Gbígbéga ni Olúwa Ọlọ́run wa  
kí a sìn ín ní òkè mímọ́ rẹ̀  
nítorí Olúwa Ọlọ́run wa jẹ́ mímọ́.