26
Orin ìyìn kan
Ní ọjọ́ náà ni a ó kọ orin yìí ní ilẹ̀ Juda.
Àwa ní ìlú alágbára kan,
Ọlọ́run fi ìgbàlà ṣe
ògiri àti ààbò rẹ̀.
Ṣí àwọn ìlẹ̀kùn
kí àwọn olódodo orílẹ̀-èdè kí ó lè wọlé,
orílẹ̀-èdè tí ó pa ìgbàgbọ́ mọ́.
Ìwọ yóò pa á mọ́ ní àlàáfíà pípé
ọkàn ẹni tí ó dúró ṣinṣin,
nítorí ó gbẹ́kẹ̀lé ọ.
Gbẹ́kẹ̀lé Olúwa títí láé,
nítorí Olúwa, Olúwa ni àpáta ayérayé náà.
Ó sọ àwọn tí ó ń gbé ní òkè di onírẹ̀lẹ̀
ó rẹ ìlú agbéraga náà nílẹ̀;
ó sọ ọ́ di ilẹ̀ pẹrẹsẹ
ó sì sọ ọ́ sílẹ̀ nínú erùpẹ̀.
Ẹsẹ̀ tẹ̀ ẹ́ mọ́lẹ̀
ẹsẹ̀ aninilára n nì,
ipasẹ̀ àwọn òtòṣì.
 
Ipa ọ̀nà àwọn olódodo tẹ́jú,
ìwọ tó dúró ṣinṣin, ìwọ mú ọ̀nà
àwọn olódodo ṣe geere.
Bẹ́ẹ̀ ni, Olúwa, rírìn ní ọ̀nà òfin rẹ
àwa dúró dè ọ́;
orúkọ rẹ àti òkìkí rẹ
àwọn ni ohun tí ọkàn wa ń fẹ́.
Ọkàn mi ń pòùngbẹẹ̀ rẹ ní ọ̀gànjọ́ òru;
ní òwúrọ̀ ni ẹ̀mí mi ń ṣàfẹ́rí rẹ.
Nígbà tí ìdájọ́ rẹ bá sọ̀kalẹ̀ sórí ayé
àwọn ènìyàn yóò kọ́ ìṣòdodo.
10 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a fi oore-ọ̀fẹ́ hàn sí àwọn ìkà
wọn kò kọ́ láti sọ òdodo;
kódà ní ilẹ̀ àwọn tí ó dúró ṣinṣin wọ́n
tẹ̀síwájú láti máa ṣe ibi
wọn kò sì ka ọláńlá Olúwa sí.
11  Olúwa, ti gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè
ṣùgbọ́n àwọn kò rí i.
Jẹ́ kí wọ́n rí ìtara rẹ fún àwọn ènìyàn rẹ
kí ojú kí ó tì wọ́n;
jẹ́ kí iná tí a fi pamọ́ fún àwọn
ọ̀tá rẹ jó wọn run.
 
12  Olúwa, ìwọ fi àlàáfíà lélẹ̀ fún wa;
ohun gbogbo tí a ti ṣe yọrí ìwọ ni
ó ṣe é fún wa.
13  Olúwa Ọlọ́run wa, àwọn olúwa mìíràn
lẹ́yìn rẹ ti jẹ ọba lé wa lórí,
ṣùgbọ́n orúkọ rẹ nìkan ni àwa fi ọ̀wọ̀ fún.
14 Wọ́n ti kú báyìí, wọn ò sí láààyè mọ́;
gbogbo ẹ̀mí tí ó ti kọjá lọ wọ̀nyí kò le dìde mọ́.
Ìwọ jẹ́ wọ́n ní ìyà o sì sọ wọ́n di asán,
ìwọ pa gbogbo ìrántí wọn rẹ́ pátápátá.
15 Ìwọ ti mú orílẹ̀-èdè gbòòrò, Olúwa;
ìwọ ti mú orílẹ̀-èdè bí sí i.
Ìwọ ti gba ògo fún ara rẹ;
ìwọ ti sún gbogbo àwọn ààlà ilẹ̀ sẹ́yìn.
 
16  Olúwa, wọ́n wá sọ́dọ̀ rẹ nínú ìpọ́njú wọn;
nígbà tí ìbáwí rẹ wà lára wọn,
wọ́n gbàdúrà kẹ́lẹ́kẹ́lẹ́.
17 Gẹ́gẹ́ bí obìnrin tí ó lóyún tí ó sì fẹ́rẹ̀ bímọ
tí í rúnra tí ó sì ń sọkún nínú ìrora rẹ̀,
bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni àwa rí níwájú rẹ Olúwa.
18 Àwa wà nínú oyún, a wà nínú ìrora,
ṣùgbọ́n, afẹ́fẹ́ ni a bí lọ́mọ.
Àwa kò mú ìgbàlà wá sí ilẹ̀ ayé;
àwa kọ́ ni a bí àwọn ènìyàn tí ó wà láyé.
 
19 Ṣùgbọ́n àwọn òkú yín yóò wà láààyè
ara wọn yóò dìde.
Ìwọ tí o wà nínú erùpẹ̀,
dìde nílẹ̀ kí o sì ké igbe ayọ̀.
Ìrì rẹ dàbí ìrì òwúrọ̀,
ayé yóò bí àwọn òkú rẹ̀ lọ́mọ.
 
20 Ẹ lọ, ẹ̀yin ènìyàn mi, ẹ wọ ìyẹ̀wù yín lọ
kí ẹ sì ti àwọn ìlẹ̀kùn lẹ́yìn yín,
ẹ fi ara yín pamọ́ fún ìgbà díẹ̀
títí tí ìbínú rẹ̀ yóò fi rékọjá.
21 Kíyèsi i, Olúwa ń jáde bọ̀ láti ibùgbé rẹ̀
láti jẹ àwọn ènìyàn ilẹ̀ ayé ní ìyà fún ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
Ayé yóò sì sọ àwọn ẹ̀jẹ̀ tí a ta sí orí rẹ̀;
kì yóò sì fi àwọn tí a ti pa pamọ́ mọ́.