27
Má ṣe yangàn nítorí ọ̀la
nítorí o kò mọ ohun tí ọjọ́ kan le è mú wáyé.
 
Jẹ́ kí ẹlòmíràn yìn ọ́ dípò ẹnu ara rẹ,
àní àlejò, kí ó má sì ṣe ètè ìwọ fúnra rẹ̀.
 
Òkúta wúwo, erùpẹ̀ sì wúwo
ṣùgbọ́n ìbínú aṣiwèrè wúwo ju méjèèjì lọ.
 
Ìbínú ni ìkà, ìrunú sì burú púpọ̀
ṣùgbọ́n ta ni ó le è dúró níwájú owú?
 
Ìbániwí gbangba sàn
ju ìfẹ́ ìkọ̀kọ̀ lọ.
 
Òtítọ́ ni ọgbẹ́ ọ̀rẹ́,
ṣùgbọ́n ìfẹnukonu ọ̀tá ni ẹ̀tàn.
 
Kódà oyin kò dùn lẹ́nu ẹni tí ó ti yó
ṣùgbọ́n òróǹró gan an dùn lẹ́nu ẹni tí ebi ń pa.
 
Bí ẹyẹ tí ó ṣáko lọ kúrò níbi ìtẹ́ rẹ̀
ni ènìyàn tí ó ṣáko lọ kúrò ní ilé rẹ̀.
 
Ìpara olóòórùn dídùn àti tùràrí ń mú ayọ̀ wá sínú ọkàn
bẹ́ẹ̀ ni inú dídùn láti ọ̀dọ̀ ọ̀rẹ́ ń wá láti inú ìmọ̀ràn tí ó ṣàkóso.
 
10 Má ṣe kọ ọ̀rẹ́ rẹ àti ọ̀rẹ́ baba rẹ sílẹ̀,
má sì ṣe lọ sílé arákùnrin rẹ nígbà tí ìdààmú dé bá ọ
ó sàn kí o jẹ́ aládùúgbò tí ó súnmọ́ ni ju arákùnrin tí ó jìnnà sí ni.
 
11 Gbọ́n, ọmọ mi, kí o sì mú ayọ̀ wá sínú ọkàn mi
nígbà náà ni mo le dá gbogbo ẹni tí ó bá kẹ́gàn mi.
 
12 Ọlọ́gbọ́n rí ewu, ó sì fi ara pamọ́
ṣùgbọ́n aláìgbọ́n rí, kàkà kí ó dúró ó tẹ̀síwájú, ó sì jìyà rẹ̀.
 
13 Gba aṣọ ẹni tí ó ṣe onídùúró fún àjèjì
fi ṣe ẹ̀rí ìdúró bí o bá ṣe onídùúró fún obìnrin oníṣekúṣe.
 
14 Bí ènìyàn kan ń kígbe súre fún aládùúgbò rẹ ní òwúrọ̀
a ó kà á sí bí èpè.
 
15 Àyà tí ó máa ń jà dàbí
ọ̀wààrà òjò ní ọjọ́ tí òjò ń rọ̀;
16 dídá a lẹ́kun dàbí ìgbà tí ènìyàn ń dá afẹ́fẹ́ lẹ́kun
tàbí bí ẹni tí ó gbá òróró.
 
17 Bí irin tí ń pọ́n irin mú
bẹ́ẹ̀ ni ènìyàn kan ń pọ́n ẹlòmíràn mú.
 
18 Ẹni tí ó tọ́jú igi ọ̀pọ̀tọ́ yóò jẹ èso rẹ̀
ẹni tí ó sì fojú tó ọ̀gá rẹ̀ yóò gba ọlá.
 
19 Bí omi tí ń ṣe àfihàn ojú, nígbà tí a bá wò ó
bẹ́ẹ̀ ni ọkàn ènìyàn ń ṣe àfihàn ènìyàn.
 
20 Kò tẹ́ ikú àti ìparun lọ́rùn rí
bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú ni ojú ènìyàn kò rí ìtẹ́lọ́rùn rí.
 
21 Iná fún fàdákà iná ìléru fún wúrà,
ṣùgbọ́n a ń dán ènìyàn wò nípa ìyìn tí ó ń gbà.
 
22 Bí a tilẹ̀ gún aláìgbọ́n nínú odó,
fi ọmọ odó gún un bí èlùbọ́
ìwọ kì yóò le è yọ ìwà òmùgọ̀ rẹ̀ kúrò ní inú rẹ̀.
 
23 Rí i dájú pé o mọ ipò tí àwọn agbo àgùntàn rẹ wà
bojútó àwọn agbo màlúù rẹ dáradára;
24 nítorí ọrọ̀ kì í pẹ́ lọ títí
adé kì í sì í wà lórí títí láéláé.
 
25 Nígbà tí a bá kó koríko, ewéko tuntun yóò sì hù jáde, a ó sì kó koríko àwọn orí òkè wọlé
26 àwọn àgùntàn yóò pèsè aṣọ fún ọ,
àti ewúrẹ́ yóò pèsè owó oko.
 
27 Ìwọ yóò ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ wàrà ewúrẹ́
láti bọ́ ọ àti ìdílé rẹ
àti láti tọ́jú àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ.