Saamu 36
Fún adarí orin. Ti Dafidi ìránṣẹ́ Olúwa. 
 
1  Ìré-òfin-kọjá ènìyàn búburú  
jẹ́ kí n mọ̀ nínú ọkàn mi pé,  
ìbẹ̀rù Ọlọ́run kò sí  
níwájú wọn.   
   
 
2 Nítorí pé wọ́n pọ́n ara wọn ní ojú ara wọn  
títí tí a kò fi le rí ẹ̀ṣẹ̀ wọn láti kórìíra.   
3 Ọ̀rọ̀ ẹnu wọn ni ẹ̀ṣẹ̀ òhun ẹ̀tàn;  
wọ́n ti fi ọgbọ́n àti ṣíṣe rere sílẹ̀.   
4 Wọ́n gbìmọ̀ ìwà ìkà nígbà tí wọ́n wà lórí ibùsùn wọn:  
wọ́n gba ọ̀nà tí kò dára  
wọn kò sì kọ ọ̀nà ibi sílẹ̀.   
   
 
5 Ìdúró ṣinṣin ìfẹ́ rẹ, ìwọ Olúwa, ó ga dé ọ̀run,  
òtítọ́ ọ̀ rẹ ga dé àwọsánmọ̀.   
6 Òdodo rẹ dàbí àwọn òkè Ọlọ́run,  
àwọn ìdájọ́ rẹ dàbí ibú ńlá;  
ìwọ gba ẹranko àti ènìyàn là, Olúwa.   
7 Báwo ni ìṣeun ìdúró ṣinṣin ìfẹ́ rẹ ti tó! Ọlọ́run!  
Kí gbogbo ọmọ ènìyàn le sá sí abẹ́ òjìji ìyẹ́ rẹ.   
8 Àsè ilé rẹ yóò tẹ́ wọn lọ́rùn gidigidi;  
ìwọ yóò sì mú wọn mu nínú odò inú dídùn rẹ.   
9 Nítorí pé pẹ̀lú rẹ ni orísun ìyè wà:  
nínú ìmọ́lẹ̀ rẹ ni àwa yóò rí ìmọ́lẹ̀.   
   
 
10 Mú ìṣeun ìfẹ́ ẹ̀ rẹ sí àwọn tí ó mọ̀ ọ́n  
àti ìgbàlà rẹ sí àwọn tí ó ní ìdúró ṣinṣin ọkàn!   
11 Má ṣe jẹ́ kí ẹsẹ̀ agbéraga kí ó wá sí orí mi,  
kí o má sì jẹ́ kí ọwọ́ àwọn ènìyàn búburú sí mi ní ipò.   
12 Níbẹ̀ ni àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ gbé ṣubú sí:  
a rẹ̀ wọ́n sílẹ̀, wọn kì yóò le è dìde!