Saamu 56
Fún adarí orin. Ti ohùn “Àdàbà lórí Óákù òkè réré.” Ti Dafidi. Miktamu. Nígbà tí àwọn ará Filistini ka mọ́ ní Gati. 
 
1 Ṣàánú fún mi, Ọlọ́run,  
nítorí àwọn ènìyàn ń fi ìgbónára lépa mi;  
ní gbogbo ọjọ́ ni wọn ń kọjú ìjà sí mi, wọn ń ni mi lára.   
2 Àwọn ọ̀tá mi ń lé mi ní gbogbo ọjọ́,  
àwọn ènìyàn ń kọjú ìjà sí mi nínú ìgbéraga wọn.   
   
 
3 Nígbà tí ẹ̀rù bà ń bà mí,  
èmi o gbẹ́kẹ̀lé ọ.   
4 Nínú Ọlọ́run èmi yóò máa yìn ọ̀rọ̀ rẹ,  
nínú Ọlọ́run ni ìgbẹ́kẹ̀lé mi; ẹ̀rù kì yóò bà mí  
kí ni ẹran-ara lè ṣe sí mi?   
   
 
5 Wọn ń yí ọ̀rọ̀ mí ní gbogbo ọjọ́,  
wọn ń gbèrò nígbà gbogbo láti ṣe mí níbi.   
6 Wọn kó ara wọn jọ, wọ́n ba.  
Wọ́n ń ṣọ́ ìgbésẹ̀ mi  
wọn ń làkàkà láti gba ẹ̀mí mi.   
7 San ẹ̀san iṣẹ́ búburú wọ́n fún wọn;  
ní ìbínú rẹ, Ọlọ́run, wọ́ àwọn ènìyàn náà bọ́ sílẹ̀.   
   
 
8 Kọ ẹkún mi sílẹ̀;  
kó omijé mi sí ìgò rẹ,  
wọ́n kò ha sí nínú ìkọ̀sílẹ̀ rẹ bí?   
9 Nígbà náà ni àwọn ọ̀tá mi yóò pẹ̀yìndà  
nígbà tí mo bá pè fún ìrànlọ́wọ́  
nípa èyí ni mo mọ̀ pé Ọlọ́run ń bẹ fún mi.   
   
 
10 Nínú Ọlọ́run, ẹni tí mo yìn ọ̀rọ̀ rẹ̀  
nínú Olúwa, ẹni tí mo yin ọ̀rọ̀ rẹ̀,   
11 nínú Ọlọ́run ni ìgbẹ́kẹ̀lé mi:  
ẹ̀rù kì yóò bà mí.  
Kí ni ènìyàn lè ṣe sí mi?   
   
 
12 Mo jẹ́ ẹ̀jẹ́ lábẹ́ rẹ Ọlọ́run:  
èmi o mú ìyìn mi wá fún ọ.   
13 Nítorí ìwọ tí gbà mí lọ́wọ́ ikú  
àti ẹsẹ̀ mi lọ́wọ́ ìṣubú,  
kí èmí lè máa rìn níwájú Ọlọ́run  
ní ìmọ́lẹ̀ àwọn alààyè.