6
Ọ̀rẹ́  
1 Níbo ni olùfẹ́ rẹ lọ,  
ìwọ arẹwà jùlọ láàrín àwọn obìnrin?  
Níbo ni olùfẹ́ rẹ yà sí,  
kí a lè bá ọ wá a?   
Olólùfẹ́  
2 Olùfẹ́ mi ti sọ̀kalẹ̀ lọ sínú ọgbà rẹ̀,  
sí ibi ibùsùn tùràrí,  
láti máa jẹ nínú ọgbà  
láti kó ìtànná lílì jọ.   
3 Èmi ni ti olùfẹ́ mi, olùfẹ́ mi sì ni tèmi,  
Ó ń jẹ láàrín ìtànná lílì.   
Olùfẹ́  
4 Ìwọ lẹ́wà olùfẹ́ mi, bí i Tirsa,  
ìwọ lẹ́wà bí i Jerusalẹmu,  
ìwọ ògo bí ogun pẹ̀lú ọ̀págun.   
5 Yí ojú rẹ kúrò lára mi;  
nítorí ojú rẹ borí mi.  
Irun rẹ rí bí i ọ̀wọ́ ewúrẹ́  
tí ó sọ̀kalẹ̀ wá láti Gileadi.   
6 Eyín rẹ rí bí ọ̀wọ́ àgùntàn,  
tí ó gòkè láti ibi ìwẹ̀ rẹ̀ wá,  
gbogbo wọn bí ìbejì,  
kò sì ṣí ọ̀kankan tí ó yàgàn nínú wọn.   
7 Ẹ̀rẹ̀kẹ́ rẹ lẹ́bàá ìbòjú rẹ,  
rí bí ẹ̀là èso pomegiranate.   
8 Ọgọ́ta ayaba ní ń bẹ níbẹ̀,  
àti ọgọ́rin àlè,  
àti àwọn wúńdíá láìníye.   
9 Àdàbà mi, aláìlábàwọ́n mi, ọ̀kan ni,  
ọ̀kan ṣoṣo ọmọbìnrin ìyá rẹ̀,  
ààyò ẹyọ kan ṣoṣo ẹni tí ó bí i.  
Àwọn obìnrin rí i wọ́n pè é ní alábùkún fún  
àwọn ayaba àti àwọn àlè gbé oríyìn fún un.   
Ọ̀rẹ́  
10 Ta ni èyí tí ó tàn jáde bí i ìràwọ̀ òwúrọ̀,  
tí ó dára bí òṣùpá, tí ó mọ́lẹ̀ bí oòrùn,  
tí ó ní ẹ̀rù bí i jagunjagun pẹ̀lú ọ̀págun?   
Olùfẹ́  
11 Èmi sọ̀kalẹ̀ lọ sí ibi ọgbà èso igi  
láti wo àwọn ẹ̀ka igi tuntun ní àfonífojì,  
láti rí i bí àjàrà rúwé,  
tàbí bí pomegiranate ti rudi.   
12 Kí èmi tó mọ̀,  
àárẹ̀ ọkàn mú mi, mo sì fẹ́ kí ń wà láàrín àwọn ènìyàn mi.   
Ọ̀rẹ́  
13 Padà wá, padà wá, ìwọ ọmọ Ṣulamati;  
padà wá, padà wá, kí àwa kí ó lè yọ́ ọ wò.  
Olùfẹ́  
Èéṣe tí ẹ̀yin fẹ́ yọ́ Ṣulamati wò,  
bí ẹni pé orin ijó Mahanaimu?