4
1 Báwo ni wúrà ṣe sọ ògo dídán rẹ̀ nù,  
wúrà dídára di àìdán!  
Òkúta ibi mímọ́ wá túká  
sí oríta gbogbo òpópó.   
   
 
2 Báwo ni àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin Sioni tí ó ṣe iyebíye,  
tí wọ́n fi wúrà dídára ṣe  
wá dàbí ìkòkò amọ̀ lásán  
iṣẹ́ ọwọ́ amọ̀kòkò!   
   
 
3 Àwọn ajáko pèsè ọmú wọn  
fún ìtọ́jú àwọn ọmọ wọn,  
ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn mi wá láì lọ́kàn  
bí ògòǹgò ní aginjù.   
   
 
4 Nítorí òǹgbẹ, ahọ́n àwọn ọmọ ọwọ́  
lẹ̀ mọ́ òkè ẹnu wọn;  
àwọn ọmọdé bẹ̀bẹ̀ fún oúnjẹ,  
ṣùgbọ́n kò sí ẹni tí ó fi fún wọn.   
   
 
5 Àwọn tí ó ń jẹ ohun dáradára  
di òtòṣì ní òpópó.  
Àwọn tí a fi aṣọ dáradára wọ̀  
ni wọ́n sùn ní orí òkìtì eérú.   
   
 
6 Ìjìyà àwọn ènìyàn mi  
tóbi ju ti Sodomu lọ,  
tí a sí ní ipò ní òjijì  
láìsí ọwọ́ láti ràn án lọ́wọ́.   
   
 
7 Ọmọ ọba ọkùnrin wọn mọ́ ju òjò-dídì,  
wọ́n sì funfun ju wàrà lọ  
wọ́n ni ìtọ́jú bí iyùn pupa,  
ìrísí wọn dàbí safire.   
   
 
8 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí wọ́n dúdú ju èédú;  
wọn kò sì dá wọn mọ̀ ní òpópó.  
Ara wọn hun mọ́ egungun;  
ó sì gbẹ bí igi gbígbẹ.   
   
 
9 Àwọn tí ó kù nípasẹ̀ idà sàn  
ju àwọn tí ìyàn pa;  
tí ó wọ àkísà ebi, tí ó ń ṣòfò  
fún àìní oúnjẹ láti inú pápá.   
   
 
10 Pẹ̀lú ọwọ́ àwọn obìnrin aláàánú  
ni wọ́n ṣe ọmọ wọn jẹ  
tí ó di oúnjẹ fún wọn  
nígbà tí a pa àwọn ènìyàn mi run.   
   
 
11 Olúwa ti fi ihò kíkún fún ìbínú rẹ̀;  
ó sì tú ìbínú gbígbóná rẹ̀ jáde.  
Ó da iná ní Sioni  
tí ó jó ìpìlẹ̀ rẹ̀ run.   
   
 
12 Àwọn ọba ayé kò gbàgbọ́,  
tàbí àwọn ènìyàn ayé,  
wí pé àwọn ọ̀tá àti aninilára le wọ  
odi ìlú Jerusalẹmu.   
   
 
13 Èyí ṣẹlẹ̀ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn wòlíì  
àti àìṣedéédéé àwọn olórí àlùfáà,  
tí ó ta ẹ̀jẹ̀ àwọn olódodo  
sílẹ̀ láàrín rẹ̀.   
   
 
14 Nísinsin yìí wọ́n ń rìn kiri ní òpópó  
bí ọkùnrin tí ó fọ́jú.  
Ẹ̀jẹ̀ ara wọn sọ wọ́n di àbàwọ́n  
tí kò sẹ́ni tó láyà láti fọwọ́ kan aṣọ wọn.   
   
 
15 “Lọ kúrò! Ẹ̀yin di aláìmọ́!” ni àwọn ènìyàn ń kígbe sí wọn.  
“Ẹ lọ! Ẹ lọ! Ẹ má ṣe fọwọ́ kàn wá!”  
Àwọn ènìyàn láàrín orílẹ̀-èdè wí pé,  
“Wọn kì yóò tẹ̀dó síbí mọ́.”   
   
 
16 Olúwa ti tú wọn ká fúnra rẹ̀;  
kò sí bojútó wọn mọ́.  
Kò sí ọ̀wọ̀ fún olórí àlùfáà mọ́,  
àti àánú fún àwọn àgbàgbà.   
   
 
17 Síwájú sí i, ojú wa kùnà  
fún wíwo ìrànlọ́wọ́ asán;  
láti orí ìṣọ́ wa ni à ń wò  
fún orílẹ̀-èdè tí kò le gbà wá là.   
   
 
18 Wọ́n ń ṣọ́ wa kiri,  
àwa kò sì le rìn ní òpópó wa mọ́.  
Òpin wa ti súnmọ́, ọjọ́ wa sì níye  
nítorí òpin wa ti dé.   
   
 
19 Àwọn tí ń lé wa yára  
ju idì ojú ọ̀run lọ;  
wọ́n lé wa ní gbogbo orí òkè  
wọ́n sì gẹ̀gùn dè wá ní aginjù.   
   
 
20 Ẹni àmì òróró Olúwa, èémí ìyè wa,  
ni wọ́n fi tàkúté wọn mú.  
Àwa rò pé lábẹ́ òjìji rẹ̀  
ni àwa yóò máa gbé láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.   
   
 
21 Ẹ yọ̀ kí inú yín sì dùn, ẹ̀yin ọmọbìnrin Edomu,  
ẹ̀yin tó ń gbé ní ilẹ̀ Usi.  
Ṣùgbọ́n, a ó gbé ago náà kọjá sọ́dọ̀ rẹ pẹ̀lú;  
ìwọ yóò yó bí ọ̀mùtí, ìwọ yóò sì rìn ní ìhòhò.   
   
 
22 Ìwọ ọmọbìnrin Sioni, ìjìyà rẹ yóò dópin;  
kò ní mú ìgbèkùn rẹ pẹ́ mọ́.  
Ṣùgbọ́n, ìwọ ọmọbìnrin Edomu, yóò jẹ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ ní yà  
yóò sì fi àìṣedéédéé rẹ hàn kedere.